2. Kro 33:1-5 Yorùbá Bibeli (YCE)

1. ẸNI ọdun mejila ni Manasse, nigbati o bẹ̀rẹ si ijọba, o si jọba ọdun marundilọgọta ni Jerusalemu:

2. Ṣugbọn o ṣe buburu li oju Oluwa, bi irira awọn orilẹ-ède, ti Oluwa le jade niwaju awọn ọmọ Israeli.

3. Nitori ti o tun kọ́ ibi giga wọnni ti Hesekiah baba rẹ̀, ti wó lulẹ, o si gbé pẹpẹ wọnni soke fun Baalimu, o si ṣe ere oriṣa, o si mbọ gbogbo ogun ọrun, o si nsìn wọn.

4. O tẹ́ pẹpẹ pẹlu ni ile Oluwa, niti eyiti Oluwa ti sọ pe; Ni Jerusalemu li orukọ mi yio wà lailai.

5. O si tẹ́ pẹpẹ fun gbogbo ogun ọrun li àgbala mejeji ile Oluwa.

2. Kro 33