Iṣe Apo 24:11-19 Yorùbá Bibeli (YCE)

11. Ki o le yé ọ pe, ijejila pére yi ni mo gòke lọ si Jerusalemu lati lọ jọsìn.

12. Bẹ̃ni nwọn kò ri mi ni tẹmpili ki emi ki o ma ba ẹnikẹni jiyàn, bẹ̃li emi kò rú awọn enia soke, ibaṣe ninu sinagogu, tabi ni ilu:

13. Bẹ̃ni nwọn kò le ladi ohun ti nwọn fi mi sùn si nisisiyi.

14. Ṣugbọn eyi ni mo jẹwọ fun ọ, pe bi Ọna ti a npè ni adamọ̀, bẹ̃li emi nsìn Ọlọrun awọn baba wa, emi ngbà nkan gbogbo gbọ́ gẹgẹ bi ofin, ati ti a kọ sinu iwe awọn woli:

15. Mo si ni ireti sipa ti Ọlọrun, eyi ti awọn tikarawọn pẹlu jẹwọ, pe ajinde okú mbọ̀, ati ti olõtọ, ati ti alaiṣõtọ.

16. Ninu eyi li emi si nṣe idaraya, lati ni ẹri-ọkàn ti kò li ẹ̀ṣẹ sipa ti Ọlọrun, ati si enia nigbagbogbo.

17. Ṣugbọn lẹhin ọdún pipọ, mo mu ọrẹ-ãnu fun orilẹ-ède mi wá, ati ọrẹ-ẹbọ.

18. Larin wọnyi ni nwọn ri mi ni iwẹnu ni tẹmpili, bẹ̃ni kì iṣe pẹlu awujọ, tabi pẹlu ariwo.

19. Ṣugbọn awọn Ju lati Asia wà nibẹ, awọn ti iba wà nihinyi niwaju rẹ, ki nwọn ki o já mi ni koro, bi nwọn ba li ohunkohun si mi.

Iṣe Apo 24