Samuẹli Kinni 12:9-18 BIBELI MIMỌ (BM)

9. Ṣugbọn wọ́n gbàgbé OLUWA Ọlọrun wọn. Wọ́n jagun, OLUWA sì fi wọ́n lé Sisera, olórí ogun Jabini ọba Hasori lọ́wọ́, àwọn ará Filistia ati ọba Moabu náà sì ṣẹgun wọn.

10. Lẹ́yìn náà, àwọn baba ńlá yín kígbe pe OLUWA fún ìrànlọ́wọ́. Wọ́n ní, ‘A ti ṣẹ̀, nítorí pé a ti kọ OLUWA sílẹ̀, a sì ń sin oriṣa Baali, ati ti Aṣitarotu. Nisinsinyii, gbà wá lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wa, a óo sì máa sìn ọ́.’

11. OLUWA bá rán Jerubaali ati Baraki, ati Jẹfuta ati èmi, Samuẹli, láti gbà yín lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá yín káàkiri, ó sì jẹ́ kí ẹ wà ní alaafia.

12. Ṣugbọn nígbà tí ẹ rí i pé Nahaṣi, ọba Amoni fẹ́ gbé ogun tì yín, ẹ kọ OLUWA lọ́ba, ẹ wí fún mi pé, ẹ fẹ́ ọba tí yóo jẹ́ alákòóso yín.

13. “Ọba tí ẹ bèèrè fún náà nìyí, ẹ̀yin ni ẹ bèèrè rẹ̀, OLUWA sì ti fun yín nisinsinyii.

14. Bí ẹ bá bẹ̀rù OLUWA, tí ẹ̀ ń sìn ín, tí ẹ̀ ń gbọ́ tirẹ̀, tí ẹ sì ń pa àwọn òfin rẹ̀ mọ́, tí ẹ̀yin ati ọba tí ń ṣe àkóso yín bá ń tẹ̀lé àwọn ìlànà OLUWA Ọlọrun yín, ohun gbogbo ni yóo máa lọ déédé fun yín.

15. Ṣugbọn bí ẹ kò bá gbọ́ ti OLUWA Ọlọrun yín, tí ẹ kò sì pa òfin rẹ̀ mọ́, yóo dojú ìjà kọ ẹ̀yin ati ọba yín.

16. Nítorí náà, ẹ dúró jẹ́ẹ́, kí ẹ wo iṣẹ́ ńlá tí OLUWA yóo ṣe.

17. Àkókò ìkórè ọkà nìyí, àbí bẹ́ẹ̀ kọ́? N óo gbadura, OLUWA yóo sì jẹ́ kí ààrá sán, kí òjò sì rọ̀. Nígbà tí èyí bá ṣẹlẹ̀, ẹ óo mọ̀ pé bíbèèrè tí ẹ bèèrè fún ọba, ẹ̀ṣẹ̀ ńlá ni ẹ dá sí OLUWA.”

18. Samuẹli bá gbadura, ní ọjọ́ náà gan-an, OLUWA sán ààrá, ó sì rọ òjò. Ẹ̀rù OLUWA ati ti Samuẹli sì ba gbogbo àwọn eniyan náà.

Samuẹli Kinni 12