Orin Solomoni 7:1-4 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Ẹsẹ̀ rẹ ti dára tó ninu bàtà,ìwọ, ọmọ aládé.Itan rẹ dàbí ohun ọ̀ṣọ́,tí ọlọ́gbọ́n oníṣọ̀nà ṣe.

2. Ìdodo rẹ dàbí abọ́,tí kì í gbẹ fún àdàlú waini,ikùn rẹ dàbí òkítì ọkà,tí a fi òdòdó lílì yíká.

3. Ọmú rẹ mejeeji dàbí ọmọ àgbọ̀nrín meji,tí wọn jẹ́ ìbejì.

4. Ọrùn rẹ dàbí ilé-ìṣọ́ tí wọn fi eyín erin kọ́.Ojú rẹ dàbí adágún omi ìlú Heṣiboni,tí ó wà ní ẹnubodè Batirabimu.Imú rẹ dàbí ilé ìṣọ́ Lẹbanoni,tí ó dojú kọ ìlú Damasku.

Orin Solomoni 7