Orin Solomoni 2:5-11 BIBELI MIMỌ (BM)

5. Fún mi ni èso àjàrà gbígbẹ jẹ,kí ara mi mókun,fún mi ní èso ápù jẹ kí ara tù mí,nítorí pé, àìsàn ìfẹ́ ń ṣe mí.

6. Ó wù mí kí ọwọ́ òsì rẹ̀ wà ní ìgbèrí mi,kí ó sì fi ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ fà mí mọ́ra.

7. Mo kìlọ̀ fun yín, ẹ̀yin ọmọbinrin Jerusalẹmu,ní orúkọ egbin, ati ti àgbọ̀nrín pé,ẹ kò gbọdọ̀ jí ìfẹ́ títí yóo fi wù ú láti jí.

8. Mo gbọ́ ohùn olùfẹ́ mi, wò ó! Ó ń bọ̀,ó ń fò lórí àwọn òkè ńlá,ó sì ń bẹ́ lórí àwọn òkè kéékèèké.

9. Olólùfẹ́ mi dàbí egbin,tabi ọ̀dọ́ akọ àgbọ̀nrín.Wò ó! Ó dúró lẹ́yìn ògiri ilé wa,ó ń yọjú lójú fèrèsé,ó ń yọjú níbi fèrèsé kékeré tí ó wà lókè.

10. Olùfẹ́ mi bá mi sọ̀rọ̀, ó wí fún mi pé,“Dìde, olùfẹ́ mi, arẹwà mi,jẹ́ kí á máa lọ.”

11. Àkókò òtútù ti lọ,òjò sì ti dáwọ́ dúró.

Orin Solomoni 2