3. Ẹ kéde ògo rẹ̀ láàrin àwọn orílẹ̀-èdè;ẹ sọ̀rọ̀ iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ láàrin àwọn eniyan.
4. Nítorí OLUWA tóbi, ó yẹ kí á máa yìn ín lọpọlọpọ;ó sì yẹ kí á bẹ̀rù rẹ̀ ju gbogbo oriṣa lọ.
5. Nítorí oriṣa lásán ni àwọn orílẹ̀-èdè yòókù ń sìn,ṣugbọn OLUWA ni ó dá ọ̀run.
6. Iyì ati ọlá ńlá ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀;agbára ati ẹwà kún inú ilé mímọ́ rẹ̀.
7. Ẹ yin OLUWA, gbogbo ẹ̀yin aráyé;ẹ kókìkí ògo ati agbára rẹ̀.
8. Ẹ fún OLUWA ní iyì tí ó tọ́ sí orúkọ rẹ̀,ẹ mú ọrẹ lọ́wọ́ wá sinu àgbàlá rẹ̀.
9. Ẹ sin OLUWA ninu ẹwà ìwà mímọ́;gbogbo ayé, ẹ wárìrì níwájú rẹ̀.
10. Ẹ wí láàrin àwọn orílẹ̀-èdè pé, “OLUWA jọba!A ti fi ìdí ayé múlẹ̀, kò sì ní yẹ̀ lae;OLUWA yóo fi òtítọ́ ṣe ìdájọ́ àwọn eniyan.”