Orin Dafidi 89:48-51 BIBELI MIMỌ (BM)

48. Ta ló wà láyé tí kò ní kú?Ta ló lè gba ẹ̀mí ara rẹ̀ lọ́wọ́ agbára isà òkú?

49. OLUWA, níbo ni ìfẹ́ rẹ ìgbàanì tí kì í yẹ̀ wà,tí o búra fún Dafidi pẹlu òtítọ́ rẹ?

50. OLUWA, ranti bí èmi, iranṣẹ rẹ, ti di ẹni yẹ̀yẹ́;ati bí mo ti ń farada ẹ̀gàn àwọn eniyan,

51. OLUWA àwọn ọ̀tá rẹ ń fi ẹni tí o fi àmì òróró yàn ṣe yẹ̀yẹ́,wọ́n sì ń kẹ́gàn ìrìn ẹsẹ̀ rẹ̀.

Orin Dafidi 89