Orin Dafidi 88:3-7 BIBELI MIMỌ (BM)

3. Nítorí pé ọkàn mi kún fún ìyọnu;mo sì súnmọ́ isà òkú.

4. Mo dàbí àwọn tí ó ń wọ ibojì lọ;mo dà bí ẹni tí kò lágbára mọ.

5. N kò yàtọ̀ sí ẹni tí a pa tì sí apá kan láàrin àwọn òkú,mo dàbí ẹni tí a pa, tí ó sùn ninu ibojì,bí àwọn tí ìwọ kò ranti mọ́,nítorí pé wọ́n ti kúrò lábẹ́ ìtọ́jú rẹ.

6. O ti fi mí sinu isà òkú tí ó jìn pupọ,ninu òkùnkùn, àní ninu ọ̀gbun.

7. Ọwọ́ ibinu rẹ wúwo lára mi,ìgbì ìrúnú rẹ sì bò mí mọ́lẹ̀.

Orin Dafidi 88