Orin Dafidi 86:5-9 BIBELI MIMỌ (BM)

5. Nítorí pé olóore ni ọ́, OLUWA,o máa ń dárí jini;ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ sì pọ̀ sí gbogbo àwọn tí ń ké pè ọ́.

6. Fetí sí adura mi, OLUWA,gbọ́ igbe ẹ̀bẹ̀ mi.

7. Ní ọjọ́ ìpọ́njú mo ké pè ọ́,nítorí pé o máa ń gbọ́ adura mi.

8. OLUWA, kò sí èyí tí ó dàbí rẹ ninu àwọn oriṣa;kò sì sí iṣẹ́ ẹni tí ó dàbí iṣẹ́ rẹ.

9. Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè tí o dá ni yóo wá,OLUWA, wọn óo máa forí balẹ̀ níwájú rẹ:wọn óo sì máa yin orúkọ rẹ lógo.

Orin Dafidi 86