Orin Dafidi 78:57-61 BIBELI MIMỌ (BM)

57. Wọ́n yipada, wọ́n sì hu ìwà ọ̀dàlẹ̀bíi ti àwọn baba ńlá wọn;wọn kò ṣe é gbẹ́kẹ̀lé, wọ́n dàbí ọfà tí ó tẹ̀.

58. Wọ́n fi ojúbọ àwọn oriṣa wọn bí i ninu;wọ́n sì fi ère wọn mú un jowú.

59. Nígbà tí Ọlọrun gbọ́, inú bí i gidigidi;ó sì kọ Israẹli sílẹ̀ patapata.

60. Ó kọ ibùgbé rẹ̀ ní Ṣilo sílẹ̀,àní, àgọ́ rẹ̀ láàrin ọmọ eniyan.

61. Ó jẹ́ kí á gbé àmì agbára rẹ̀ lọ sí ìgbèkùn;ó sì fi ògo rẹ̀ lé ọ̀tá lọ́wọ́.

Orin Dafidi 78