10. Nígbà náà ni mo wí pé, “Ohun tí ó bà mí lọ́kàn jẹ́ ni péỌ̀gá Ògo kò jẹ́wọ́ agbára mọ́.”
11. N óo ranti àwọn iṣẹ́ OLUWA,àní, n óo ranti àwọn iṣẹ́ ìyanu ìgbàanì.
12. N óo máa ṣe àṣàrò lórí gbogbo iṣẹ́ rẹ;n óo sì máa ronú lórí àwọn iṣẹ́ ribiribi tí o ṣe.
13. Ọlọrun, mímọ́ ni ọ̀nà rẹ;oriṣa wo ni ó tó Ọlọrun wa?
14. Ìwọ ni Ọlọrun tí ń ṣe ohun ìyanu;o ti fi agbára rẹ hàn láàrin àwọn eniyan.
15. O ti fi agbára rẹ gba àwọn eniyan rẹ là;àní, àwọn ọmọ Jakọbu ati Josẹfu.
16. Nígbà tí omi òkun rí ọ, Ọlọrun,àní, nígbà tí omi òkun fi ojú kàn ọ́,ẹ̀rù bà á;ibú omi sì wárìrì.
17. Ìkùukùu da omi òjò sílẹ̀,ojú ọ̀run sán ààrá;mànàmáná ń kọ yẹ̀rì káàkiri.
18. Ààrá ń sán kíkankíkan ní ojú ọ̀run,mànàmáná ń kọ yànràn, gbogbo ayé sì mọ́lẹ̀;ilẹ̀ ayé wárìrì, ó sì mì tìtì.
19. Ọ̀nà rẹ wà lójú omi òkun,ipa ọ̀nà rẹ la omi òkun ńlá já;sibẹ ẹnìkan kò rí ipa ẹsẹ̀ rẹ.
20. O kó àwọn eniyan rẹ jáde bí agbo ẹran,o fi Mose ati Aaroni ṣe olórí wọn.