Orin Dafidi 52:2-7 BIBELI MIMỌ (BM)

2. Ò ń pète ìparun;ẹnu rẹ dàbí abẹ tí ó mú, ìwọ alárèékérekè.

3. O fẹ́ràn ibi ju ire lọ,o sì fẹ́ràn irọ́ ju òtítọ́ lọ.

4. O fẹ́ràn gbogbo ọ̀rọ̀ ìbàjẹ́,Ìwọ ẹlẹ́tàn!

5. Nítòótọ́ Ọlọrun óo bá ọ kanlẹ̀,yóo gbá ọ mú, yóo sì fà ọ́ já kúrò ninu ilé rẹ;yóo fà ọ́ tu kúrò lórí ilẹ̀ alààyè.

6. Nígbà tí àwọn olódodo bá rí i, ẹ̀rù óo bà wọ́n,wọn óo fi rẹ́rìn-ín, wọn óo sì wí pé,

7. “Wo ẹni tí ó kọ̀, tí kò fi Ọlọrun ṣe ààbò rẹ̀,ṣugbọn ó gbẹ́kẹ̀lé ọrọ̀ rẹ̀ tí ó pọ̀,ati jamba tí ó ń ta fún ẹlòmíràn.”

Orin Dafidi 52