Orin Dafidi 50:14-17 BIBELI MIMỌ (BM)

14. Ọpẹ́ ni kí ẹ fi rúbọ sí Ọlọrun,kí ẹ sì máa san ẹ̀jẹ́ yín fún Ọ̀gá Ògo.

15. Ẹ ké pè mí ní ọjọ́ ìṣòro;n óo gbà yín, ẹ óo sì yìn mí lógo.”

16. Ṣugbọn Ọlọrun bi àwọn eniyan burúkú pé,“Ẹ̀tọ́ wo ni ẹ níláti máa ka àwọn òfin mi,tabi láti máa mú ẹnu ba ìlànà mi?

17. Nítorí ẹ kórìíra ẹ̀kọ́;ẹ sì ti ta àṣẹ mi nù.

Orin Dafidi 50