14. Ọpẹ́ ni kí ẹ fi rúbọ sí Ọlọrun,kí ẹ sì máa san ẹ̀jẹ́ yín fún Ọ̀gá Ògo.
15. Ẹ ké pè mí ní ọjọ́ ìṣòro;n óo gbà yín, ẹ óo sì yìn mí lógo.”
16. Ṣugbọn Ọlọrun bi àwọn eniyan burúkú pé,“Ẹ̀tọ́ wo ni ẹ níláti máa ka àwọn òfin mi,tabi láti máa mú ẹnu ba ìlànà mi?
17. Nítorí ẹ kórìíra ẹ̀kọ́;ẹ sì ti ta àṣẹ mi nù.