Orin Dafidi 50:10-20 BIBELI MIMỌ (BM)

10. Nítorí èmi ni mo ni gbogbo ẹran inú igbó,tèmi sì ni gbogbo mààlúù tó wà lórí ẹgbẹrun òkè.

11. Gbogbo ẹyẹ ojú ọ̀run ni mo mọ̀,tèmi sì ni gbogbo nǹkan tí ń rìn ninu pápá.

12. “Bí ebi bá tilẹ̀ pa mí, ẹ̀yin kọ́ ni n óo sọ fún,nítorí èmi ni mo ni gbogbo ayé ati àwọn nǹkan tí ó wà ninu rẹ̀.

13. Ṣé èmi a máa jẹ ẹran akọ mààlúù?Àbí mà máa mu ẹ̀jẹ̀ ewúrẹ́?

14. Ọpẹ́ ni kí ẹ fi rúbọ sí Ọlọrun,kí ẹ sì máa san ẹ̀jẹ́ yín fún Ọ̀gá Ògo.

15. Ẹ ké pè mí ní ọjọ́ ìṣòro;n óo gbà yín, ẹ óo sì yìn mí lógo.”

16. Ṣugbọn Ọlọrun bi àwọn eniyan burúkú pé,“Ẹ̀tọ́ wo ni ẹ níláti máa ka àwọn òfin mi,tabi láti máa mú ẹnu ba ìlànà mi?

17. Nítorí ẹ kórìíra ẹ̀kọ́;ẹ sì ti ta àṣẹ mi nù.

18. Tí ẹ bá rí olè, ẹ̀yin pẹlu rẹ̀ a dọ̀rẹ́;ẹ sì ń bá àwọn panṣaga kẹ́gbẹ́.

19. “Ọ̀rọ̀ ibi dùn lẹ́nu yín pupọ;ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn sì yọ̀ létè yín.

20. Ẹ̀ ń jókòó sọ̀rọ̀ arakunrin yín níbi:ẹ̀ ń sọ̀rọ̀ ìbàjẹ́ nípa ọmọ ìyá yín.

Orin Dafidi 50