Orin Dafidi 5:9-12 BIBELI MIMỌ (BM)

9. Nítorí kò sí òtítọ́ kan lẹ́nu wọn;ìparun ni ó wà ninu ọkàn wọn.Isà òkú tí ó yanu sílẹ̀ ni ọ̀fun wọn;ẹnu wọn kún fún ìpọ́nni ẹ̀tàn.

10. Dá wọn lẹ́bi, Ọlọrun, kí o sì fìyà jẹ wọ́n;jẹ́ kí ìgbìmọ̀pọ̀ wọn ó gbé wọn ṣubú.Ta wọ́n nù nítorí ọ̀pọ̀ ìrékọjá wọn,nítorí pé wọ́n ṣọ̀tẹ̀ sí ọ.

11. Ṣugbọn jẹ́ kí inú gbogbo àwọn tí ó sá di ọ́ ó dùn,kí wọn ó máa kọrin ayọ̀ títí lae.Dáàbò bò wọ́n,kí àwọn tí ó fẹ́ràn orúkọ rẹ sì máa yọ̀ ninu rẹ.

12. Nítorí ìwọ OLUWA a máa bukun àwọn olódodo;ò sì máa fi ojurere rẹ tí ó dàbí apata dáàbò bò wọ́n.

Orin Dafidi 5