10. N óo fi gbogbo ara wí pé,“OLUWA, ta ni ó dàbí rẹ?Ìwọ ni ò ń gba aláìlágbáralọ́wọ́ ẹni tí ó lágbáratí o sì ń gba aláìlágbára ati aláìnílọ́wọ́ ẹni tí ó fẹ́ fi wọ́n ṣe ìjẹ.”
11. Àwọn tí ń fi ìlara jẹ́rìí èké dìde sí mi;wọ́n ń bi mí léèrè ohun tí n kò mọ̀dí.
12. Wọ́n fi ibi san oore fún mi,ọkàn mi sì rẹ̀wẹ̀sì.
13. Bẹ́ẹ̀ sì ni, ní tèmi, nígbà tí wọn ń ṣàìsàn,aṣọ ọ̀fọ̀ ni mo wọ̀;mo fi ààwẹ̀ jẹ ara mi níyà;mo gbadura pẹlu ìtẹríba patapata,
14. bí ẹni pé mò ń ṣọ̀fọ̀ ọ̀rẹ́ mi, tabi arakunrin mi;mò ń lọ káàkiri, bí ẹni tí ń pohùnréré ẹkún ìyá rẹ̀,mo doríkodò, mo sì ń ṣọ̀fọ̀.
15. Ṣugbọn nígbà tí èmi kọsẹ̀, wọ́n kó ara wọn jọ,wọ́n ń yọ̀,wọ́n kó tì mí;pàápàá jùlọ, àwọn àlejò tí n kò mọ̀ ríbẹ̀rẹ̀ sí purọ́ mọ́ mi léraléra.
16. Wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí pẹ̀gàn mi, wọ́n ń fi mí ṣe ẹlẹ́yà;wọ́n sì ń wò mí bíi pé kí n kú.
17. OLUWA, yóo ti pẹ́ tó, tí o óo máa wò mí níran?Yọ mí kúrò ninu ogun tí wọn gbé tì mí,gbà mí kúrò lọ́wọ́ àwọn kinniun!
18. Nígbà náà ni n óo dúpẹ́ lọ́wọ́ rẹ láàrin àwùjọ ọ̀pọ̀ eniyan;láàrin ọpọlọpọ eniyan ni n óo máa yìn ọ́.
19. Má jẹ́ kí àwọn tí ń bá mi ṣọ̀tá láìnídìí yọ̀ mí,má sì jẹ́ kí àwọn tí ó kórìíra mi wò mí ní ìwò ẹ̀sín.
20. Nítorí pé wọn kì í sọ̀rọ̀ alaafia sí àwọn tí wọn ń lọ jẹ́ẹ́jẹ́ wọnàfi kí wọ́n máa pète oríṣìíríṣìí ẹ̀tàn.
21. Wọ́n la ẹnu, wọ́n ń pariwo lé mi lórí,wọ́n ń wí pé, “Ìn hín ìn, a rí ọ, ojú wa ló ṣe!”
22. O ti rí i, OLUWA, má dákẹ́.OLUWA, má jìnnà sí mi.