Orin Dafidi 33:9-15 BIBELI MIMỌ (BM)

9. Nítorí pé OLUWA sọ̀rọ̀, ayé wà;ó pàṣẹ, ayé sì dúró.

10. OLUWA sọ ìmọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè di asán;ó sì mú kí ètò àwọn eniyan já sófo.

11. Ètò OLUWA wà títí lae,èrò ọkàn rẹ̀ sì wà láti ìran dé ìran.

12. Ayọ̀ ń bẹ fún orílẹ̀-èdè tí OLUWA jẹ́ Ọlọrun wọn,àní àwọn eniyan tí ó yàn gẹ́gẹ́ bí ìní rẹ̀!

13. OLUWA bojúwo ilẹ̀ láti ọ̀run,ó rí gbogbo eniyan;

14. láti orí ìtẹ́ rẹ̀ tí ó gúnwà sí,ó wo gbogbo aráyé.

15. Òun ni ó dá ọkàn gbogbo wọn,tí ó sì ń mójútó gbogbo ìṣe wọn.

Orin Dafidi 33