Orin Dafidi 32:3-7 BIBELI MIMỌ (BM)

3. Nígbà tí n kò jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ mi,ó rẹ̀ mí wá láti inú,nítorí kíkérora tí mò ń kérora ní gbogbo ìgbà.

4. Nítorí tọ̀sán-tòru ni o fi ń jẹ mí níyà;gbogbo agbára mi ló lọ háú,bí omi tíí gbẹ lákòókò ẹ̀ẹ̀rùn.

5. Mo jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ mi fún ọ;n kò sì fi àìdára mi pamọ́ fún ọ.Mo ní, “Èmi óo jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ mi fún Oluwa,”o sì dáríjì mí.

6. Nítorí náà, kí gbogbo olódodo máa gbadura sí ọ;ní àkókò tí ìpọ́njú bá ń yí lura wọn bí ìṣàn omi ńlá,kò ní dé ọ̀dọ̀ wọn.

7. Ìwọ ni ibi ìsásí mi;o pa mí mọ́ kúrò ninu ìṣòro;o sì fi ìgbàlà yí mi ká.

Orin Dafidi 32