Orin Dafidi 31:1-4 BIBELI MIMỌ (BM)

1. OLUWA, ìwọ ni mo sá di,má jẹ́ kí ojú tì mí lae;gbà mí, nítorí olóòótọ́ ni ọ́.

2. Dẹ etí sí mi, yára gbà mí.Jẹ́ àpáta ààbò fún mi;àní ilé ààbò tó lágbára láti gbà mí là.

3. Ìwọ ni àpáta ati ilé ààbò mi;nítorí orúkọ rẹ, máa tọ́ mi kí o sì máa fọ̀nà hàn mí.

4. Yọ mí kúrò ninu àwọ̀n tí wọ́n dẹ pamọ́ dè mí,nítorí ìwọ ni ẹni ìsádi mi.

Orin Dafidi 31