Orin Dafidi 24:5-10 BIBELI MIMỌ (BM)

5. Òun ni yóo rí ibukun gbà lọ́dọ̀ OLUWA,tí yóo sì rí ìdáláre gbà lọ́wọ́ Ọlọrun, Olùgbàlà rẹ̀.

6. Irú wọn ni àwọn tí ń wá OLUWA,àní àwọn tí ń wá ojurere Ọlọrun Jakọbu.

7. Ẹ ṣí sílẹ̀ gbayau, ẹ̀yin ìlẹ̀kùn,ẹ wà ní ṣíṣí sílẹ̀, ẹ̀yin ìlẹ̀kùn ayérayé,kí Ọba ògo lè wọlé.

8. Ta ni Ọba ògo yìí?OLUWA tí ó ní ipá tí ó sì lágbára,OLUWA tí ó lágbára lógun.

9. Ẹ ṣí sílẹ̀ gbayau, ẹ̀yin ìlẹ̀kùn,ẹ wà ní ṣíṣí sílẹ̀, ẹ̀yin ìlẹ̀kùn ayérayé,kí Ọba ògo lè wọlé.

10. Ta ni Ọba ògo yìí?OLUWA àwọn ọmọ ogun,òun ni Ọba ògo náà.

Orin Dafidi 24