9. Òun ni ó ń fún àwọn ẹranko ní oúnjẹ,tí ó sì ń bọ́ ọmọ ẹyẹ ìwò, tí ó ń ké.
10. Kì í ṣe agbára ẹṣin ni inú rẹ̀ dùn sí,kì í sì í ṣe inú agbára eniyan ni ayọ̀ rẹ̀ wà.
11. Ṣugbọn inú OLUWA dùn sí àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀,àwọn tí ó ní ìrètí ninu ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀.
12. Gbé OLUWA ga, ìwọ Jerusalẹmu!Yin Ọlọrun rẹ, ìwọ Sioni!
13. Ó fún ẹnubodè rẹ ní agbára,ó sì bukun àwọn tí ń gbé inú rẹ.
14. Ó jẹ́ kí alaafia wà ní ààlà ilẹ̀ rẹ,ó sì fi oúnjẹ tí ó dára bọ́ ọ lábọ̀ọ́yó.
15. Ó pàṣẹ lórí ilẹ̀ ayé,àṣẹ rẹ̀ sì múlẹ̀ kíá.
16. Ó da òjò dídì bo ilẹ̀ bí ẹ̀gbọ̀n òwú,ó sì fọ́n ìrì dídì ká bí eérú.
17. Ó sọ yìnyín sílẹ̀ bí òkò,ta ni ó lè fara da òtútù rẹ̀?
18. Ó sọ̀rọ̀, wọ́n yọ́,ó fẹ́ afẹ́fẹ́, omi sì bẹ̀rẹ̀ sí ṣàn.
19. Ó ṣí ọ̀rọ̀ rẹ̀ payá fún Jakọbu,ó sì fi òfin ati ìlànà rẹ̀ han Israẹli.