Orin Dafidi 145:8-12 BIBELI MIMỌ (BM)

8. Aláàánú ni OLUWA, olóore sì ni;kì í yára bínú, ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀ sì pọ̀.

9. OLUWA ṣeun fún gbogbo eniyan,àánú rẹ̀ sì ń bẹ lórí gbogbo ohun tí ó dá.

10. OLUWA, gbogbo ohun tí o dá ni yóo máa dúpẹ́ lọ́wọ́ rẹ,àwọn eniyan mímọ́ rẹ yóo sì máa yìn ọ́.

11. Wọn óo máa ròyìn ògo ìjọba rẹ,wọn óo sì máa sọ nípa agbára rẹ,

12. láti mú àwọn eniyan mọ agbára rẹ,ati ẹwà ògo ìjọba rẹ.

Orin Dafidi 145