Orin Dafidi 14:2-6 BIBELI MIMỌ (BM)

2. OLUWA bojú wo ilẹ̀, láti ọ̀run wá,ó wo àwọn ọmọ eniyan,láti mọ̀ bí àwọn kan bá wà tí wọ́n gbọ́n,tí wọn ń wá Ọlọrun.

3. Gbogbo wọn ti ṣìnà,gbogbo wọn pátá ni wọ́n sì ti bàjẹ́;kò sí ẹnìkan tí ń ṣe rere,kò sí ẹyọ ẹnìkan ṣoṣo.

4. Ṣé gbogbo àwọn aṣebi kò gbọ́n ni?Àwọn tí ń jẹ eniyan mi bí ẹni jẹun,àwọn tí kì í ké pe OLUWA.

5. Níbẹ̀ ni a óo ti dẹ́rù bà wọ́n gidigidi,nítorí Ọlọrun ń bẹ pẹlu àwọn olódodo.

6. Ẹ̀yin ń fẹ́ da ètò aláìní rú,ṣugbọn OLUWA ni ààbò rẹ̀.

Orin Dafidi 14