Orin Dafidi 120:1-6 BIBELI MIMỌ (BM)

1. OLUWA ni mo ké pè, nígbà tí mo wà ninu ìpọ́njú,ó sì dá mi lóhùn.

2. OLUWA, gbà mí lọ́wọ́ àwọn èké,ati lọ́wọ́ àwọn ẹlẹ́tàn.

3. Kí ni a óo fi san án fun yín?Kí ni a óo sì ṣe si yín, ẹ̀yin ẹlẹ́tàn?

4. Ọfà mímú ni a óo ta yín,a óo sì dáná sun yín.

5. Mo gbé! Nítorí pé mo dàbí àlejò tó wọ̀ ní Meṣeki,tí ń gbé ààrin àwọn àgọ́ Kedari.

6. Ó pẹ́ jù tí mo tí ń bá àwọn tí ó kórìíra alaafia gbé.

Orin Dafidi 120