32. Kí wọn gbé e ga láàrin ìjọ eniyan,kí wọn sì yìn ín ní àwùjọ àwọn àgbà.
33. Ó sọ odò di aṣálẹ̀,ó sọ orísun omi di ilẹ̀ gbígbẹ,
34. ó sọ ilẹ̀ eléso di aṣálẹ̀ oníyọ̀,nítorí ìwà burúkú àwọn tí ń gbé inú rẹ̀.
35. Ó sọ aṣálẹ̀ di adágún omi,ó sì sọ ilẹ̀ gbígbẹ di orísun omi.
36. Ó jẹ́ kí àwọn tí ebi ń pa máa gbé ibẹ̀,wọ́n sì tẹ ìlú dó, láti máa gbé.
37. Wọ́n dáko, wọ́n gbin àjàrà,wọ́n sì kórè lọpọlọpọ.
38. Ó bukun wọn, ó mú kí wọn bí sí i lọpọlọpọ,kò sì jẹ́ kí ẹran ọ̀sìn wọ́n dínkù.
39. Nígbà tí wọ́n dínkù, tí a rẹ̀ wọ́n sílẹ̀,nípa ìnira, ìpọ́njú, ati ìṣòro,
40. ó da ẹ̀gàn lu àwọn ìjòyè,ó sì mú kí wọn máa rìn kiri ní aṣálẹ̀,níbi tí kò sí ọ̀nà.
41. Ṣugbọn ó yọ aláìní kúrò ninu ìpọ́njú,ó sì mú kí ìdílé wọn pọ̀ sí i bí agbo ẹran.
42. Àwọn olódodo rí i, inú wọn dùn,a sì pa àwọn eniyan burúkú lẹ́nu mọ́.
43. Kí ẹni tí ó gbọ́n kíyèsí nǹkan wọnyi;kí ó sì fi òye gbé ìfẹ́ OLUWA tí kì í yẹ̀.