Orin Dafidi 106:43-47 BIBELI MIMỌ (BM)

43. Ọpọlọpọ ìgbà ni ó gbà wọ́n sílẹ̀,ṣugbọn wọ́n ti pinnu láti máa tàpá sí i,OLUWA sì rẹ̀ wọ́n sílẹ̀ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn.

44. Sibẹsibẹ, ninu ìnira wọn, ó ṣàánú wọn,nígbà tí ó gbọ́ igbe wọn.

45. Nítorí tiwọn, ó ranti majẹmu tí ó dá,ó sì yí ìpinnu rẹ̀ pada nítorí ọ̀pọ̀ ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀.

46. Ó jẹ́ kí àánú wọn ṣe gbogbo àwọn tí ó kó wọn ní ìgbèkùn.

47. Gbà wá, OLUWA, Ọlọrun wa,kí o sì kó wa kúrò láàrin àwọn orílẹ̀-èdè mìíràn,kí á lè máa fi ọpẹ́ fún orúkọ mímọ́ rẹ,kí á sì lè máa ṣògo ninu ìyìn rẹ.

Orin Dafidi 106