Orin Dafidi 106:40-44 BIBELI MIMỌ (BM)

40. Nígbà náà ni inú bí OLUWA sí àwọn eniyan rẹ̀,ó sì kórìíra àwọn ẹni ìní rẹ̀.

41. Ó fi wọ́n lé àwọn orílẹ̀-èdè mìíràn lọ́wọ́,títí tí àwọn tí ó kórìíra wọn fi jọba lé wọn lórí.

42. Àwọn ọ̀tá wọn ni wọ́n lára,wọ́n sì fi agbára mú wọn sìn.

43. Ọpọlọpọ ìgbà ni ó gbà wọ́n sílẹ̀,ṣugbọn wọ́n ti pinnu láti máa tàpá sí i,OLUWA sì rẹ̀ wọ́n sílẹ̀ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn.

44. Sibẹsibẹ, ninu ìnira wọn, ó ṣàánú wọn,nígbà tí ó gbọ́ igbe wọn.

Orin Dafidi 106