2. Ẹ kọrin sí i, ẹ kọ orin ìyìn sí i,ẹ sọ nípa gbogbo iṣẹ́ ribiribi rẹ̀.
3. Ẹ máa fi orúkọ mímọ́ rẹ̀ yangàn,kí ọkàn àwọn tí ń wá OLUWA ó máa yọ̀.
4. Ẹ wá ojurere OLUWA ati agbára rẹ̀,ẹ máa wá ojurere rẹ̀ nígbà gbogbo.
5. Ẹ ranti iṣẹ́ ribiribi tí ó ti ṣe,ẹ ranti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ ati ìdájọ́ rẹ̀.
6. Ẹ̀yin ọmọ Abrahamu, iranṣẹ rẹ̀,ẹ̀yin ọmọ Jakọbu, àyànfẹ́ rẹ̀.
7. OLUWA ni Ọlọrun wa,ìdájọ́ rẹ̀ kárí gbogbo ayé.
8. Títí lae ni ó ń ranti majẹmu rẹ̀,ó ranti àṣẹ tí ó pa fún ẹgbẹẹgbẹrun ìran,
9. majẹmu tí ó bá Abrahamu dá,ìlérí tí ó fi ìbúra ṣe fún Isaaki,
10. tí ó fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ fún Jakọbu gẹ́gẹ́ bí òfin,àní fún Israẹli gẹ́gẹ́ bíi majẹmu ayérayé,