Orin Dafidi 104:14-19 BIBELI MIMỌ (BM)

14. Ó ń mú kí koríko dàgbà fún àwọn ẹran láti jẹ,ati ohun ọ̀gbìn fún ìlò eniyan,kí ó lè máa mú oúnjẹ jáde láti inú ilẹ̀;

15. ati ọtí waini tí ń mú inú eniyan dùn,ati epo tí ń mú ojú eniyan dán,ati oúnjẹ tí ń fún ara lókun.

16. Àwọn igi OLUWA ń mu omi ní àmutẹ́rùn,àní àwọn igi kedari Lẹbanoni tí ó gbìn.

17. Lórí wọn ni àwọn ẹyẹ ń tẹ́ ìtẹ́wọn sí,àkọ̀ sì ń kọ́ ilé rẹ̀ sórí igi firi.

18. Òkè gíga ni ilé ewúrẹ́ igbó,abẹ́ àpáta sì ni ibùgbé ehoro.

19. O dá òṣùpá láti máa sàmì àkókò,oòrùn sì mọ àkókò wíwọ̀ rẹ̀.

Orin Dafidi 104