Nọmba 31:1-4 BIBELI MIMỌ (BM)

1. OLUWA sọ fún Mose pé,

2. “Fìyà jẹ àwọn ará Midiani fún ohun tí wọ́n ṣe sí àwọn ọmọ Israẹli. Lẹ́yìn náà, o óo kú.”

3. Mose bá sọ fún àwọn eniyan náà pé, “Ẹ múra ogun kí á lè gbógun ti àwọn ará Midiani, kí á sì fìyà jẹ wọ́n fún ohun tí wọ́n ṣe sí OLUWA.

4. Ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan yóo mú ẹgbẹrun eniyan wá fún ogun náà.”

Nọmba 31