Nọmba 24:2-6 BIBELI MIMỌ (BM)

2. ó sì rí i bí àwọn ọmọ Israẹli ti pa àgọ́ wọn, olukuluku ẹ̀yà ni ààyè tirẹ̀. Ẹ̀mí Ọlọrun sì bà lé e,

3. ó sì bẹ̀rẹ̀ sí fi òwe sọ̀rọ̀, ó ní,“Ọ̀rọ̀ Balaamu ọmọ Beori nìyí,ọ̀rọ̀ ẹni tí ó ríran dájúdájú;

4. ìran ẹni tí ó ń gbọ́ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run,mo sì lajú sílẹ̀ kedere rí ìran láti ọ̀dọ̀ Olodumare.Nítòótọ́ ó ṣubú, ṣugbọn ojú rẹ̀ wà ní ṣíṣí sílẹ̀.

5. Báwo ni àgọ́ rẹ ti dára tó ìwọ Jakọbu,ati ibùdó rẹ ìwọ Israẹli!

6. Ó dàbí àfonífojì tí ó tẹ́ lọ bẹẹrẹ,bí ọgbà tí ó wà lẹ́bàá odò.Ó dàbí àwọn igi aloe tí OLUWA gbìn,ati bí igi kedari tí ó wà lẹ́bàá odò.

Nọmba 24