Nahumu 1:6-11 BIBELI MIMỌ (BM)

6. Bí ó bá ń bínú ta ló lè dúró?Ta ló lè farada ibinu gbígbóná rẹ̀?Ìrúnú rẹ̀ a máa ru jáde bí ahọ́n iná,a sì máa fọ́ àwọn àpáta níwájú rẹ̀.

7. OLUWA ṣeun,òun ni ibi ààbò ní ọjọ́ ìdààmú;ó sì mọ àwọn tí wọn ń sálọ sọ́dọ̀ rẹ̀ fún ààbò.

8. Bí odò tí ó kún bo bèbè rẹ̀ni yóo ṣe mú ìparun bá àwọn ọ̀tá rẹ̀;yóo sì lépa àwọn ọ̀tá rẹ̀ bọ́ sí inú òkùnkùn.

9. Èrò ibi wo ni ẹ̀ ń gbà sí OLUWA?Yóo wulẹ̀ pa yín run patapata ni;kò sì sí ẹni tí OLUWA yóo gbẹ̀san lára rẹ̀ lẹ́ẹ̀kantí yóo lè ṣẹ̀ ẹ́ lẹẹkeji.

10. Wọn yóo jóná bí igbó ẹlẹ́gùn-ún tí ó dí,àní bíi koríko gbígbẹ.

11. Ṣebí ọ̀kan ninu yín ni ó ń gbìmọ̀ burúkú sí OLUWA, tí ó sì ń fúnni ní ìmọ̀ràn burúkú?

Nahumu 1