1. Nítorí náà Dafidi pàṣẹ pé, “Ibí yìí ni ilé OLUWA Ọlọrun, ati pẹpẹ ẹbọ sísun yóo wà fún Israẹli.”
2. Dafidi pàṣẹ pé kí gbogbo àwọn àjèjì tí wọn ń gbé ilẹ̀ Israẹli péjọ, ó bẹ̀rẹ̀ sí kó wọn ṣiṣẹ́, ara wọn ni wọ́n gbẹ́ òkúta fún kíkọ́ tẹmpili.
3. Ó kó ọpọlọpọ irin jọ, tí wọn óo fi rọ ìṣó, tí wọn yóo fi kan àwọn ìlẹ̀kùn ati ìdè, ó kó idẹ jọ lọpọlọpọ pẹlu, ju ohun tí ẹnikẹ́ni lè wọ̀n lọ,