Kronika Kinni 11:25-32 BIBELI MIMỌ (BM)

25. Ó di olókìkí láàrin àwọn ọgbọ̀n ọ̀gágun; ṣugbọn òkìkí tirẹ̀ kò tó ti àwọn akọni mẹta náà. Dafidi bá fi ṣe olórí àwọn tí ń ṣọ́ ọba.

26. Àwọn olókìkí mìíràn ninu àwọn ọmọ ogun Dafidi nìwọ̀nyí: Asaheli, arakunrin Joabu; ati Elihanani, ọmọ Dodo, ará Bẹtilẹhẹmu;

27. Ṣamotu, láti Harodu;

28. Helesi, láti inú ìdílé Peloni, Ira, ọmọ Ikeṣi ará Tekoa, ati Abieseri, láti Anatoti

29. Sibekai, láti inú ìdílé Huṣati, ati Ilai, láti inú ìdílé Aho;

30. Maharai, ará Netofa, ati Helodi, ọmọ Baana, ará Netofa;

31. Itai, ọmọ Ribai, ará Gibea, láti inú ẹ̀yà Bẹnjamini, ati Bẹnaya, ará Piratoni;

32. Hurai, ará etí odò Gaaṣi, ati Abieli, ará Aribati;

Kronika Kinni 11