5. Ọlọrun ìbá ya ẹnu rẹ̀,kí ó sọ̀rọ̀ sí ọ.
6. Kì bá jẹ́ fi àṣírí ọgbọ́n hàn ọ́,nítorí ìmọ̀ rẹ̀ pọ̀ lọpọlọpọ.Mọ̀ dájú pé ìyà tí Ọlọrun fi jẹ ọ́kò to nǹkan lẹ́gbẹ̀ẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ.
7. “Ǹjẹ́ o lè wádìí àwọn ohun ìjìnlẹ̀ nípa Ọlọrun?Tabi kí o tọpinpin Olodumare?
8. Ó ga ju ọ̀run lọ, kí lo lè ṣe sí i?Ó jìn ju isà òkú lọ, kí lo lè mọ̀ nípa rẹ̀?
9. Ó gùn ju ayé lọ,Ó sì fẹ̀ ju òkun lọ.
10. Tí ó bá ń kọjá lọ, tí ó sì ti eniyan mọ́lé,tí ó pe olúwarẹ̀ lẹ́jọ́,ta ló lè yẹ̀ ẹ́ lọ́wọ́ wò?
11. Nítorí ó mọ àwọn eniyan lásán,ṣé bí ó bá rí ẹ̀ṣẹ̀,kí ó má ṣe akiyesi rẹ̀?
12. Ó di ìgbà tí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ bá bí ọmọ rẹ̀ ní eniyan,kí òmùgọ̀ eniyan tó gbọ́n.
13. “Bí o bá fi ọkàn rẹ sí ohun tí ó tọ́,o óo lè nawọ́ sí i.
14. Bí o bá ń dẹ́ṣẹ̀, má dẹ́ṣẹ̀ mọ́,má sì ṣe jẹ́ kí ìwà burúkú, wà ní ọwọ́ rẹ.
15. Nígbà náà ni o óo tó lè fi ìgboyà gbójú sókè láìlẹ́bi;o óo wà láìléwu,o kò sì ní bẹ̀rù.