Jeremaya 31:27-31 BIBELI MIMỌ (BM)

27. OLUWA ní, “Ọjọ́ ń bọ̀ tí n óo kó àtènìyàn, àtẹranko kún ilẹ̀ Israẹli ati ilẹ̀ Juda.

28. Nígbà tí àkókò bá tó, gẹ́gẹ́ bí mo tí ń ṣọ́ wọn tí mo fi fà wọ́n tu, tí mo wó wọn lulẹ̀, tí mo bì wọ́n wó, tí mo pa wọ́n run, tí mo sì mú kí ibi ó bá wọn; bẹ́ẹ̀ ni n óo ṣọ́ wọn tí n óo fi kọ́ àwọn ìlú wọn tí n óo sì fìdí wọn múlẹ̀. Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.

29. Tó bá dìgbà náà, àwọn eniyan kò ní máa wí mọ́ pé,‘Àwọn baba ni wọ́n jẹ èso àjàrà kíkan,àwọn ọmọ wọn ni eyín kan.’

30. Kàkà bẹ́ẹ̀ ẹni tí ó bá jẹ èso àjàrà kíkan,òun ni eyín yóo kan.Olukuluku ni yóo kú nítorí ẹ̀ṣẹ̀ ara rẹ̀.

31. “Ọjọ́ ń bọ̀, tí ń óo bá ilé Israẹli ati ilé Juda dá majẹmu titun.

Jeremaya 31