Jeremaya 13:24-27 BIBELI MIMỌ (BM)

24. N óo fọn yín ká bí ìyàngbòtí afẹ́fẹ́ láti inú aṣálẹ̀ ń fẹ́ kiri.

25. Èyí ni ìpín yín,ìpín tí mo ti yàn fun yín,nítorí pé ẹ ti gbàgbé èmi OLUWA, ẹ sì gbẹ́kẹ̀lé ọlọrun èké.

26. Èmi gan-an ni n óo ká aṣọ lára yín,n óo sì fi bò yín lójú, kí ayé lè rí ìhòòhò yín.

27. Mo ti rí ìwà ìbàjẹ́ yín,gbogbo ìwà àgbèrè yín, bí ẹ tí ń yan ká bí akọ ẹṣin,ati ìwà ìṣekúṣe yín ní orí àwọn òkè ninu pápá.Ẹ̀yin ará Jerusalẹmu, ẹ gbé!Yóo ti pẹ́ tó kí á tó wẹ̀ yín mọ́?

Jeremaya 13