Heberu 1:6-11 BIBELI MIMỌ (BM)

6. Ṣugbọn nígbà tí ó mú àkọ́bí rẹ̀ wọ inú ayé, ohun tí ó sọ ni pé,“Kí gbogbo àwọn angẹliỌlọrun foríbalẹ̀ fún un.”

7. Ohun tí ó sọ nípa àwọn angẹli ni pé,“Ẹni tí ó ṣe àwọn angẹli rẹ̀ ní ẹ̀fúùfù,tí ó ṣe àwọn òjíṣẹ́ rẹ̀ ní ọwọ́ iná.”

8. Ṣugbọn ohun tí ó sọ fún Ọmọ náà ni pé,“Ìfẹ́ rẹ wà títí laelae, Ọlọrun,ọ̀pá òtítọ́ ni ọ̀pá ìjọba rẹ.

9. O fẹ́ràn òdodo, o kórìíra ẹ̀ṣẹ̀.Nítorí èyí, Ọlọrun, àní Ọlọrun rẹ, fi òróró yàn ọ́láti gbé ọ ga ju àwọn ẹgbẹ́ rẹ lọ.”

10. Ó tún sọ pé,“O ti wà láti ìṣẹ̀dálẹ̀ ayé, Oluwa,ìwọ ni o fi ìpìlẹ̀ ayé lélẹ̀.Iṣẹ́ ọwọ́ rẹ ni àwọn ọ̀run.

11. Wọn óo parẹ́ ṣugbọn ìwọ óo wà títí.Gbogbo wọn óo gbó bí aṣọ.

Heberu 1