Ẹkún Jeremaya 5:1-15 BIBELI MIMỌ (BM)

1. OLUWA, ranti ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí wa,Ṣe akiyesi ẹ̀sín wa.

2. Àwọn ilẹ̀ àjogúnbá ẹni ẹlẹ́ni,ilé wa sì ti di ti àwọn àjèjì.

3. A ti di aláìníbaba, ọmọ òrukànàwọn ìyá wa kò yàtọ̀ sí opó.

4. Owó ni a fi ń ra omi tí à ń mu,rírà ni a sì ń ra igi tí a fi ń dáná.

5. Àwọn tí wọn ń lépa wa ti bá wa,ó ti rẹ̀ wá, a kò sì ní ìsinmi.

6. A ti fa ara wa kalẹ̀ fún àwọn ará Ijipti ati àwọn ará Asirianítorí oúnjẹ tí a óo jẹ.

7. Àwọn baba wa ni wọ́n dẹ́ṣẹ̀, àwọn sì ti kú,ṣugbọn àwa ni à ń jìyà ẹ̀ṣẹ̀ wọn.

8. Àwọn ẹrú ní ń jọba lé wa lórí,kò sì sí ẹni tí yóo gbà wá lọ́wọ́ wọn.

9. Ẹ̀mí wa ni à ń fi wéwu, kí á tó rí oúnjẹ,nítorí ogun tí ó wà ninu aṣálẹ̀.

10. Awọ ara wa gbóná bí iná ààrò,nítorí ìyàn tí ó mú lọpọlọpọ.

11. Tipátipá ni wọ́n fi ń bá àwọn obinrin lòpọ̀ ní Sioni,ati àwọn ọmọbinrin tí wọn kò tíì mọ ọkunrin ní Juda.

12. Wọ́n fi okùn so ọwọ́ àwọn olórí rọ̀,wọn kò sì bọ̀wọ̀ fún àwọn àgbààgbà.

13. Wọ́n fi ipá mú àwọn ọdọmọkunrin pé kí wọn máa lọ ọlọ,àwọn ọmọde ru igi títí àárẹ̀ mú wọn!

14. Àwọn àgbààgbà ti sá kúrò ní ẹnubodè;àwọn ọdọmọkunrin sì ti dákẹ́ orin kíkọ.

15. Inú wa kò dùn mọ́;ijó wa ti yipada, ó ti di ọ̀fọ̀.

Ẹkún Jeremaya 5