Ẹkún Jeremaya 1:15-17 BIBELI MIMỌ (BM)

15. “OLUWA ti fi ẹsẹ̀ tẹ àwọn akọni mi mọ́lẹ̀;ó pe ọpọlọpọ eniyan jọ sí mi,ó ní kí wọ́n pa àwọn ọdọmọkunrin mi;OLUWA ti tẹ àwọn ọmọ Juda ní àtẹ̀rẹ́,bí ẹni tẹ èso àjàrà fún ọtí waini.

16. “Nítorí àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ wọnyi ni mo ṣe sọkún;tí omijé ń dà lójú mi;olùtùnú jìnnà sí mi,kò sí ẹni tí ó lè dá mi lọ́kàn le.Àwọn ọmọ mi ti di aláìní,nítorí pé àwọn ọ̀tá ti borí wa.

17. “Sioni na ọwọ́ rẹ̀ fún ìrànwọ́,Ṣugbọn kò sí ẹni tí ó ràn án lọ́wọ́,OLUWA ti pàṣẹ pé,kí àwọn aládùúgbò Jakọbu di ọ̀tá rẹ̀;Jerusalẹmu sì ti di eléèérí láàrin wọn.

Ẹkún Jeremaya 1