Ẹkún Jeremaya 1:1-3 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Ẹ wò ó bí ìlú tí ó kún fún eniyan tẹ́lẹ̀ ti di ahoro,tí ó wá dàbí opó!Ìlú tí ó tóbi láàrin àwọn orílẹ̀-èdè tẹ́lẹ̀!Tí ó sì dàbí ọmọ ọba obinrinláàrin àwọn ìlú yòókù.Ó ti wá di ẹni àmúsìn.

2. Ó ń sọkún tẹ̀dùntẹ̀dùn lóru,omijé ń dà lójú rẹ̀,kò sì sí ẹni tí yóo tù ú ninu, láàrin àwọn alajọṣepọ rẹ̀.Gbogbo àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ ti dà á,wọ́n dìtẹ̀ mọ́ ọn,wọ́n sì di ọ̀tá rẹ̀.

3. Juda ti lọ sí ìgbèkùn,wọ́n sì ń fi tipátipá mú un sìn.Nisinsinyii, ó ń gbéààrin àwọn orílẹ̀-èdè mìíràn,kò sì ní ibi ìsinmi.Ọwọ́ àwọn tí wọn ń lépa rẹ̀ ti tẹ̀ ẹ́,ninu ìdààmú rẹ̀.

Ẹkún Jeremaya 1