5. Bẹ́ẹ̀ ni OLUWA ṣe di ọba ní Jeṣuruni,nígbà tí gbogbo àwọn olórí péjọ,àní, gbogbo àwọn olórí ninu ẹ̀yà Israẹli.
6. Mose súre fún ẹ̀yà Reubẹni, ó ní:“Ẹ̀yà Reubẹni yóo máa wà ni, kò ní parun,àwọn eniyan rẹ̀ kò ní dínkù.”
7. Ó súre fún ẹ̀yà Juda pé:“OLUWA, gbọ́ igbe ẹ̀yà Juda,nígbà tí wọ́n bá pè fún ìrànwọ́,sì kó wọn pada sọ́dọ̀ àwọn eniyan wọn.Fi ọwọ́ ara rẹ jà fún wọn,sì ràn wọ́n lọ́wọ́ láti borí àwọn ọ̀tá wọn.”
8. Ó súre fún ẹ̀yà Lefi pé:“OLUWA, fún Lefi, ẹni tíí ṣe olódodo, ní Tumimu ati Urimu rẹ;Lefi, tí o dánwò ní Masa,tí o sì bá jà níbi odò tí ó wà ní Meriba;