Àwọn Ọba Kinni 12:27-30 BIBELI MIMỌ (BM)

27. Ó ní, “Bí àwọn eniyan wọnyi bá ń lọ rúbọ ní ilé OLUWA ní Jerusalẹmu, ọkàn gbogbo wọ́n lè tipa bẹ́ẹ̀ pada sẹ́yìn Rehoboamu, oluwa wọn; wọn óo sì pa mí, wọn óo sì pada tọ Rehoboamu, ọba Juda, lọ.”

28. Jeroboamu lọ gba àmọ̀ràn, ó bá fi wúrà yá ère akọ mààlúù meji, ó sì wí fún àwọn eniyan rẹ̀ pé, “Ẹ̀yin ọmọ Israẹli, ó pẹ́ tí ẹ ti ń lọ rúbọ ní Jerusalẹmu. Ó tó gẹ́ẹ́! Ọlọrun yín, tí ó ko yín jáde wá láti ilẹ̀ Ijipti nìyí.”

29. Ó gbé ọ̀kan kalẹ̀ ní ìlú Bẹtẹli ó sì gbé ekeji sí ìlú Dani.

30. Ọ̀rọ̀ yìí di ẹ̀ṣẹ̀ sí wọn lọ́rùn nítorí pé àwọn eniyan náà bẹ̀rẹ̀ sí lọ sí ìlú Bẹtẹli ati ìlú Dani láti jọ́sìn.

Àwọn Ọba Kinni 12