Àwọn Ọba Kinni 12:16-19 BIBELI MIMỌ (BM)

16. Nígbà tí gbogbo Israẹli rí i pé, ọba kò gbọ́ tiwọn, wọ́n dá a lóhùn pé,“Kí ló kàn wá pẹlu ìdílé Dafidi?Kí ló dà wá pọ̀ pẹlu ọmọ Jese?Ẹ̀yin ọmọ Israẹli, ẹ pada sílé yín,kí Dafidi máa bojútó ilé rẹ̀!”

17. Gbogbo Israẹli bá pada sílé wọn; ṣugbọn Rehoboamu ń jọba lórí àwọn ọmọ Israẹli tí wọ́n wà ní ilẹ̀ Juda.

18. Lẹ́yìn náà, Rehoboamu ọba rán Adoniramu, tí ó jẹ́ ọ̀gá àgbà àwọn tí wọn ń kó àwọn eniyan ṣiṣẹ́ tipátipá, láti lọ bá àwọn ọmọ Israẹli, wọ́n sì sọ ọ́ ní òkúta pa. Rehoboamu bá múra kíá, ó bọ́ sinu kẹ̀kẹ́ ogun rẹ̀, ó sá lọ sí Jerusalẹmu.

19. Láti ìgbà náà ni Israẹli ti ń bá ìdílé Dafidi ṣọ̀tẹ̀ títí di òní yìí.

Àwọn Ọba Kinni 12