8. Ẹ mú àwọn eniyan mi jáde,àwọn tí wọ́n ní ojú, ṣugbọn tí ojú wọn ti fọ́,wọ́n ní etí, ṣugbọn etí wọn ti di.
9. Jẹ́ kí gbogbo orílẹ̀-èdè péjọ,kí àwọn eniyan àgbáyé parapọ̀.Èwo ninu wọn ni ó lè kéde irú àsọtẹ́lẹ̀ yìí,tí ó lè fi àwọn ohun àtijọ́ hàn wá;kí wọn pe ẹlẹ́rìí wọn wá, kí á lè mọ̀ pé ẹjọ́ wọn tọ́,kí àwọn ẹlòmíràn lè gbọ́, kì wọn sì jẹ́rìí pé, “Òtítọ́ ni.”
10. OLUWA ní, “Ẹ̀yin ni ẹlẹ́rìí mi,ẹ̀yin ni iranṣẹ mi tí mo yàn;kí ẹ lè mọ̀ mí, kí ẹ sì gbà mí gbọ́,kí ó sì ye yín pé, Èmi ni.A kò dá Ọlọrun kankan ṣáájú mi,òmíràn kò sì ní wáyé lẹ́yìn mi.
11. “Èmi ni OLUWA,kò sí olùgbàlà kan, yàtọ̀ sí mi.
12. Mo ti sọ̀rọ̀ ìṣípayá, mo ti gba eniyan là,mo sì ti kéde,nígbà tí kò sí Ọlọrun àjèjì láàrin yín;ẹ̀yin sì ni ẹlẹ́rìí mi.Èmi OLUWA ni mo sọ bẹ́ẹ̀.
13. Èmi ni Ọlọrun,láti ìsinsìnyìí lọ, Èmi ni.Kò sí ẹnìkan tí ó lè gba eniyan kalẹ̀ lọ́wọ́ mi:Ta ni le dínà ohun tí mo bá níí ṣe?”
14. OLUWA, Ẹni Mímọ́ Israẹli, Olùràpadà yín, ní,“N óo ranṣẹ sí Babiloni nítorí yín,n óo dá gbogbo ọ̀pá ìlẹ̀kùn ibodè,ariwo ẹ̀rín àwọn ará Kalidea yóo sì di ẹkún.
15. Èmi ni OLUWA, Ẹni Mímọ́ yín,Ẹlẹ́dàá Israẹli, Ọba yín.”
16. OLUWA tí ó la ọ̀nà sí ojú òkun,tí ó la ọ̀nà lórí agbami ńlá;
17. ẹni tí ó kó kẹ̀kẹ́ ogun ati ẹṣin jáde, ogun, ati àwọn ọmọ-ogun;wọ́n dùbúlẹ̀ wọn kò lè dìde mọ́,wọ́n kú bí iná fìtílà.
18. ÓLUWA ní, “Ẹ gbàgbé àwọn ohun àtijọ́,kí ẹ sì mú ọkàn kúrò ninu ohun tí ó ti kọjá.
19. Ẹ wò ó! Mò ń ṣe nǹkan titunó ti yọ jáde nisinsinyii,àbí ẹ kò ṣe akiyesi rẹ̀?N óo la ọ̀nà ninu aginjù,n óo sì mú kí omi máa ṣàn ninu aṣálẹ̀.
20. Àwọn ẹranko ìgbẹ́ yóo máa yìn mí lógo,ati àwọn ọ̀fàfà ati ògòǹgò;nítorí pé mo ti ṣe odò ńlá fún wọn ninu aṣálẹ̀,kí àwọn àyànfẹ́ mi lè máa rí omi mu:
21. Àwọn tí mo fọwọ́ mi dá fún ara mi,kí wọ́n lè kéde ògo mi.