Aisaya 2:6-16 BIBELI MIMỌ (BM)

6. Nítorí o ti ta àwọn eniyan rẹ nù,àní, ìdílé Jakọbu.Nítorí pé àwọn aláfọ̀ṣẹ ará ìhà ìlà oòrùn pọ̀ láàrin wọn,àwọn alásọtẹ́lẹ̀ sì pọ̀ bíi ti àwọn ará Filistini,Wọ́n ti gba àṣà àwọn àjèjì.

7. Wúrà ati fadaka kún ilẹ̀ wọn,ìṣúra wọn kò sì lópin.Ẹṣin kún ilẹ̀ wọn,kẹ̀kẹ́ ogun wọn kò sì lóǹkà.

8. Ilẹ̀ wọn kún fún oriṣa,wọ́n ń bọ iṣẹ́ ọwọ́ ara wọn,wọ́n ń wólẹ̀ fún ohun tí wọ́n fọwọ́ ara wọn ṣe.

9. Bẹ́ẹ̀ ni eniyan ṣe tẹ ara rẹ̀ lórí batí ó sì rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀.Oluwa, máṣe dárí ẹ̀ṣẹ̀ wọn jì wọ́n.

10. Ẹ wọnú àpáta lọ,kí ẹ sì farapamọ́ sinu ilẹ̀.Ẹ sá fún ibinu OLUWAati ògo ọlá ńlá rẹ̀.

11. A óo rẹ ọlọ́kàn gíga eniyan sílẹ̀,a óo sì rẹ àwọn onigbeeraga sílẹ̀;OLUWA nìkan ni a óo gbéga ní ọjọ́ náà.

12. Nítorí OLUWA àwọn ọmọ ogun ti ya ọjọ́ kan sọ́tọ̀,tí yóo dojú ìjà kọ àwọn agbéraga,ati àwọn ọlọ́kàn gíga,ati gbogbo nǹkan tí à ń gbéga.

13. Yóo dojú kọ gbogbo igi Kedari ti Lẹbanoni,tí ó ga fíofío, ati gbogbo igi oaku ilẹ̀ Baṣani;

14. ati gbogbo àwọn òkè ńláńlá,ati gbogbo òkè gíga,

15. ati gbogbo ilé-ìṣọ́ gígaati gbogbo odi tí ó lágbára,

16. ati gbogbo ọkọ̀ ojú omi láti ìlú Taṣiṣi,ati gbogbo ọkọ̀ tí ó dára.

Aisaya 2