Máàkù 14:32-36 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

32. Nígbà tí wọ́n dé ibi kan tí wọ́n ń pè ní ọgbà Gétísémánì. Jésù wí fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ pé, “Ẹ jókòó dè mí níhìnín títí n ó fi lọ gbàdúrà.”

33. Ó sì mú Pétérù àti Jákọ́bù àti Jòhánù lọ pẹ̀lú rẹ̀. Òun sì kún fún ìrẹ̀wẹ̀sì àti ìbànújẹ́ gidigidi.

34. Ó sì wí fún wọn pé, “Títí dé kú. Ẹ dúró níhìnín kí ẹ sì máa mi sọ́nà.”

35. Ó sì lọ ṣíwájú díẹ̀, ó dojú bolẹ̀, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí i gbàdúrà pé, bí ó bá ṣe e ṣe kí wákàtí tí ó bọ̀ náà ré òun kọjá.

36. Ó sì wí pé, “Á bà Baba, ìwọ lè ṣe ohun gbogbo, mú ago yìí kúrò lórí mi, ṣùgbọ́n kìí ṣe èyí tí èmi fẹ́, bí kò se èyí tí ìwọ fẹ́.”

Máàkù 14