Jóòbù 39:14-22 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

14. Ó yé ẹ̀yìn rẹ̀ sílẹ̀ lórí ilẹ̀,a sì mú wọn gbóná nínú ekuru;

15. Tí ó sì gbàgbé pé, ẹ̀sẹ̀ lè tẹ̀ wọ́nfọ́, tàbí pé ẹranko ìgbẹ́ lè tẹ̀ wọ́n fọ́.

16. Kò ní àánú sí àwọn ọmọ rẹ̀ bíẹni pé wọn kì í ṣe tirẹ̀; asán ni iṣẹ́ rẹ̀, láì ní ìbẹ̀rù;

17. Nítorí pé Ọlọ́run kò fún-un ní ọgbọ́n,bẹ́ẹ̀ ni kò sì fi ìpín òye fún un.

18. Nígbà tí ó gbé ara sókè, ó ganẹṣin àti ẹlẹ́ṣin.

19. “Ìwọ ni ó fi agbára fún ẹṣin bí? tàbí ṣéÌwọ ni ó fi gọ̀gọ̀ wọ ọrùn rẹ̀ ní aṣọ?

20. Ìwọ le mú fò sókè bí ẹlẹ́ǹgà?Ògo èémí imú rẹ ní ẹ̀rù ńlá;

21. Ó fi ẹsẹ̀ halẹ̀ nínú àfonífojì, ó sì yọ̀ síagbára rẹ̀; ó lọ jáde láti pàdé àwọn ìhámọ́ra ogun.

22. Ó fi ojú kékeré wo ẹ̀rù, àyà kòsì fòó; bẹ́ẹ̀ ni kì í sì í padà ṣẹ́yìn kúrò lọ́wọ́ idà.

Jóòbù 39