11. Àpapọ̀ ọdún Énọ́sì jẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rún-ọdún-ó-lé-márùn-ún (905), ó sì kú.
12. Nígbà tí Kénánì di àádọ́rin ọdún (70) ni ó bí Máhálálélì:
13. Lẹ́yìn tí ó bí Máhálálélì, ó wà láàyè fún òjìlélẹ́gbẹ̀rín ọdún (840), ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbínrin.
14. Àpapọ̀ ọjọ́ rẹ̀ jẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rún-ó-lé-mẹ́wàá ọdún (910), ó sì kú.
15. Nígbà tí Máhálálélì pé ọmọ àrúnlélọ́gọ́ta ọdún (65) ni ó bí Járédì.
16. Máhálálélì sì gbé fún ẹgbẹ̀rin-ó-lé-ọgbọ̀n ọdún (830) lẹ́yìn ìgbà tí ó bí Járédì, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin.
17. Àpapọ̀ iye ọdún rẹ̀ jẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ̀gbẹ̀rún-ọdún-ó-dín-márùn-ún (895), ó sì kú.
18. Nígbà tí Járédì pé ọmọ ọgọ́jọ-ó-lé-méjì ọdún (162) ni ó bí Énọ́kù.
19. Lẹ́yìn èyí, ó wà láàyè fún ẹgbẹ̀rin ọdún (800) ó sì bí àwọn ọmọkúnrin àti ọmọbìnrin.
20. Àpapọ̀ ọdún rẹ̀ sì jẹ́ ẹgbẹ̀rún-dín-méjìdínlógójì (962); ó sì kú.
21. Nígbà tí Énọ́kù pé ọmọ ọgọ́ta-ó-lé-márùn ọdún (65) ni ó bí Mètúsẹ́là.
22. Lẹ́yìn tí ó bí Mètúsẹ́là, Énọ́kù sì bá Ọlọ́run rìn ní ọ̀ọ́dúnrún ọdún (300), ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin.
23. Àpapọ̀ ọjọ́ Énọ́kù sì jẹ́ irínwó-dín-márùndínlógójì-ọdún (365).
24. Énọ́kù bá Ọlọ́run rìn: a kò sì rí i mọ́ nítorí Ọlọ́run mú un lọ.
25. Nígbà tí Mètúsẹ́là pé igba-ó-dín-mẹ́talá ọdún (187) ní o bí Lámékì.
26. Lẹ́yìn èyí ó wà láàyè fún ẹgbẹ̀rin-dín-méjìdínlógún ọdún (782), ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin.
27. Àpapọ̀ ọdún Mètúsẹ́là jẹ́ ẹgbẹ̀rún-ọdún-ó-dín-mọ́kànlélọ́gbọ̀n (969), ó sì kú.