Jẹ́nẹ́sísì 36:11-14 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

11. Àwọn ọmọ Élífásì ni ìwọ̀nyí:Témánì, Ómárì, Ṣéfò, Gátamù, àti Kénásì.

12. Élífásì ọmọ Ísọ̀ sì tún ní àlè tí a ń pè ní Tímúnà pẹ̀lú, òun ló bí Ámálékì fún un. Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ-ọmọ Ádà aya Ísọ̀.

13. Àwọn ọmọ Rúélì:Náhátì, Ṣérà, Ṣámà àti Mísà. Àwọn ni ọmọ-ọmọ Báṣémátì aya Ísọ̀.

14. Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Óhólíbámà ọmọbìnrin Ánà ọmọ-ọmọ Ṣíbéónì: tí ó bí fún Ísọ̀:Jéúsì, Jálámì àti Kórà.

Jẹ́nẹ́sísì 36